ILÉ ÌṢỌ́—Ẹ̀DÀ TÓ WÀ FÚN ÌKẸ́KỌ̀Ọ́ December 2016

Àwọn àpilẹ̀kọ tá a máa kẹ́kọ̀ọ́ láti January 30 sí February 26, 2017 ló wà nínú Ilé Ìṣọ́ yìí.

ÌTÀN ÌGBÉSÍ AYÉ

Mo Di “Ohun Gbogbo fún Ènìyàn Gbogbo”

Àwọn iṣẹ́ tí Denton Hopkinson ti ṣe nínú ìjọsìn Jèhófà látọdún yìí wá ti jẹ́ kó rí bí Jèhófà ṣe ń fa àwọn èèyàn láti ibi gbogbo sínú ètò rẹ̀.

Ọlọ́run Dá Wa Sílẹ̀ Nípasẹ̀ Inú Rere Àìlẹ́tọ̀ọ́sí

Á ṣe ẹ́ láǹfààní gan-⁠an tó o bá ń ronú nípa bí Jéhófà ṣe dá ẹ sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀.

“Gbígbé Èrò Inú Ka Ẹ̀mí Túmọ̀ Sí Ìyè àti Àlàáfíà”

Ìmọ̀ràn tí ìwé Róòmù orí 8 gbà wá máa jẹ́ ká ní ìpín nínú èrè tí Jèhófà máa fún aráyé.

Ǹjẹ́ O Rántí?

Ṣó o ti ka àwọn ìwé ìròyìn Ilé Ìṣọ́ tó jáde lẹ́nu àìpẹ́ yìí? Wò ó bóyá wàá lè dáhùn àwọn ìbéèrè tá a mú látinu Bíbélì.

Kó Gbogbo Àníyàn Rẹ Lé Jèhófà

Àwọn ìgbà kan wà táwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run ní ìdààmú ọkàn. Nǹkan mẹ́rin wà tó o lè ṣe táá jẹ́ kó o ní “àlàáfíà Ọlọ́run.”

Jèhófà Máa Ń Sẹ̀san fún Àwọn Tó Ń Fi Taratara Wá A

Báwo ni ìrètí tá a ní pé Jèhófà máa san wá lẹ́san ṣe ń ṣe wá láǹfààní? Báwo ló ṣe san àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lẹ́san láyé àtijọ́, báwo ló sì ṣe ń ṣe bẹ́ẹ̀ lóde òní?

Jẹ́ Oníwà Tútù​—Ohun Tó Bọ́gbọ́n Mu Ni

Kò rọrùn láti gba ìwọ̀sí mọ́ra, síbẹ̀ Bíbélì rọ àwa Kristẹni pé ká jẹ́ oníwà tútù. Kí ló máa jẹ́ kó o níwà tútù?

Atọ́ka Àwọn Àkòrí fún Ilé Ìṣọ́ 2016

Àwọn àpilẹ̀kọ tá a tẹ̀ jáde nínú ẹ̀dà Ilé Ìṣọ́ tá à ń fi sóde àtèyí tó wà fún ìkẹ́kọ̀ọ́ tá a tò ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí.