Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

BÍBÉLÌ MÁA Ń YÍ ÌGBÉSÍ AYÉ ÀWỌN ÈÈYÀN PA DÀ

“Ó Ṣe Mí Bíi Pé Gbogbo Ohun Tí Mo Fẹ́ Lọwọ́ Mi Ti Tẹ̀”

“Ó Ṣe Mí Bíi Pé Gbogbo Ohun Tí Mo Fẹ́ Lọwọ́ Mi Ti Tẹ̀”
  • ỌDÚN TÍ WỌ́N BÍ MI: 1962

  • ORÍLẸ̀-ÈDÈ MI: Kánádà

  • IRÚ ẸNI TÍ MO JẸ́ TẸ́LẸ̀: Oníṣekúṣe

ÌGBÉSÍ AYÉ MI ÀTẸ̀YÌNWÁ

 Ìlú Montreal ni wọ́n bí mi sí, ìlú yìí ló tóbi jù ní ìpínlẹ̀ Quebec lórílẹ̀-èdè Kánádà. Àwọn òbí mi tọ́ èmi, ẹ̀gbọ́n mi àtàwọn àbúrò mi méjèèjì dàgbà ní àdúgbò Rosemont, àdúgbò tó dùn ún gbé ni. Àwọn òbí mi nífẹ̀ẹ́ wa, a jọ rọra ń gbé ayé wa jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́, a sì wà lálàáfíà.

 Láti kékeré ló ti wù mí láti kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Mo rántí ìgbà tí mò ń ka ìtàn ìgbésí ayé Jésù nínú Májẹ̀mú Tuntun lọ́mọ ọdún méjìlá [12], mo gbádùn ẹ̀ gan-an. Bí Jésù ṣe nífẹ̀ẹ́ àwọn míì, tó sì káàánú wọn wú mi lórí gan-an, ó sì wù mí kí n fìwà jọ ọ́. Àmọ́ ó ṣeni láàánú pé bí mo ṣe ń dàgbà ni èrò dáadáa tí mo ní yìí bẹ̀rẹ̀ sí í yí pa dà, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí í bá àwọn tí kò yẹ kẹ́gbẹ́.

 Bàbá mi mọ bí wọ́n ṣe ń fi saxophone kọrin, wọ́n sì pa dà fún mi ní saxophone tí wọ́n fi ń kọrin yẹn. Àmọ́ ìyẹn nìkan kọ́ ni mo jogún lára wọn, wọ́n tún jẹ́ kí n nífẹ̀ẹ́ orin gan-an débi pé orin kíkọ wá gbà mí lọ́kàn. Mo gbádùn orin kíkọ gan-an débi pé kò pẹ́ tí mo fi mọ guitar ta. Nígbà tó yá, èmi àtàwọn ọ̀rẹ́ mi mélòó kan bẹ̀rẹ̀ sí í jọ kọrin, a sì lọ kọrin láwọn àríyá kan. Bó ṣe di pé àwọn gbajúgbajà kan tó ń ṣe orin jáde kíyè sí mi nìyẹn, tí wọ́n sì wá bá mi pé àwọn máa bá mi gbé orin mi lárugẹ. Mo gbà láti bá iléeṣẹ́ ńlá kan tó ń ṣe orin jáde ṣiṣẹ́. Orin mi wá di ìlúmọ̀ọ́ká, kódà léraléra ni wọ́n máa ń kọ ọ́ lórí rédíò ní Quebec.

 Ó ṣe mí bíi pé gbogbo ohun tí mo fẹ́ lọwọ́ mi ti tẹ̀. Ọ̀dọ́ ni mí, mo tún gbajúmọ̀, ohun tí mo fẹ́ràn ni mo fi ń ṣiṣẹ́ ṣe, mo sì ń rówó gan-an nídìí ẹ̀. Lójúmọmọ, ibi tí wọ́n ti ń ṣeré ìmárale ni mo máa ń wà, àwọn èèyàn máa ń fọ̀rọ̀ wá mi lẹ́nu wò, mo máa ń buwọ́ lu ìwé táwọn èèyàn bá mú wá bá mi, iléeṣẹ́ tẹlifíṣọ̀n sì máa ń gbé mi sáyé. Tó bá wá dalẹ́, màá lọ kọrin, màá sì ṣàríyá. Nígbà tí mo ṣì kéré, ṣe ni mo máa ń mutí kí n lè máa mórí àwọn tó gba tèmi yá, àmọ́ mo bẹ̀rẹ̀ sí í lo oògùn olóró nígbà tó yá. Ṣe ni mo kàn ń ṣe bó ṣe wù mí, mo sì ya oníṣekúṣe.

 Ó máa ń wu àwọn kan kí wọ́n dà bí mi torí mo jọ ẹni tó ń láyọ̀ lójú wọn. Àmọ́ nínú lọ́hùn-ún, mi ò láyọ̀ rárá. Ó sábà máa ń ṣe mí bẹ́ẹ̀ tí mo bá dá wà. Ìbànújẹ́ dorí mi kodò, ọkàn mi ò sì balẹ̀. Ẹ̀dùn ọkàn gbáà ló jẹ́ pé ìgbà tí ọwọ́ mi mókè tán ni méjì nínú àwọn tó ń bá mi ṣe orin jáde kó àrùn AIDS, tí wọ́n sì gbabẹ̀ kú. Ẹ̀rù bà mí gan-an! Bó tiẹ̀ jẹ́ pé mo nífẹ̀ẹ́ orin, ìgbésí ayé táwọn olórin ń gbé máa ń kó mi nírìíra.

BÍ BÍBÉLÌ ṢE YÍ ÌGBÉSÍ AYÉ MI PA DÀ

 Mo rí towó ṣe lóòótọ́, mo sì gbajúmọ̀, àmọ́ mo mọ̀ pé kì í ṣe bó ṣe yẹ kí nǹkan rí láyé ló rí yìí. Kí ló dé tí ìwà ìrẹ́jẹ pọ̀ tó báyìí? Ó ń yà mí lẹ́nu bí Ọlọ́run ò ṣe wá nǹkan ṣe sí i. Kódà, mo sábà máa ń gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kó jẹ́ kí n rí ìdáhùn sáwọn ìbéèrè mi. Mo lọ gbafẹ́ nígbà kan, mo wá ní kí n sinmi díẹ̀, ibi tí mo ti ń sinmi ni mo tún ti bẹ̀rẹ̀ sí í ka Bíbélì. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ nínú nǹkan tí mò ń kà ni ò yé mi, ibi tí mo parí èrò sí ni pé òpin ayé ti sún mọ́lé.

 Nígbà tí mò ń ka Bíbélì, mo ka ibì kan tí Bíbélì ti sọ pé ìgbà kan wà tí Jésù gbààwẹ̀ ogójì [40] ọjọ́ nínú aṣálẹ̀. (Mátíù 4:​1, 2) Mo wá rò ó lọ́kàn ara mi pé témi náà bá ṣe bẹ́ẹ̀, bóyá Ọlọ́run á fi ara rẹ̀ hàn mí. Ni mo bá mú ọjọ́ tí mo máa bẹ̀rẹ̀ ààwẹ̀ ọ̀hún. Nígbà tó ku ọ̀sẹ̀ méjì kí n bẹ̀rẹ̀, Ẹlẹ́rìí Jèhófà méjì kan ilẹ̀kùn mi, mo sì ní kí wọ́n wọlé, àfi bíi pé mo ti ń retí wọn tẹ́lẹ̀. Mo wo ojú ọ̀kan nínú wọn tó ń jẹ́ Jacques, mo sì bi í pé, “Báwo la ṣe máa mọ̀ bóyá a ti ń gbé ní àwọn ọjọ́ ìkẹyìn ayé yìí?” Ló bá ṣí Bíbélì ẹ̀, ó sì ka 2 Tímótì 3:​1-5. Mo tún da ọ̀pọ̀ ìbéèrè míì bo àwọn méjèèjì, ìdáhùn tí wọ́n fún mi bọ́gbọ́n mu, ó tẹ́ mi lọ́rùn, inú Ìwé Mímọ́ ni wọ́n sì ti mú gbogbo ohun tí wọ́n sọ. Ìyẹn wú mi lórí gan-an. Lẹ́yìn ẹ̀ẹ̀mélòó kan tí wọ́n wá sílé mi, mo rí i pé mi ò nílò ààwẹ̀ kankan.

 Àwọn Ẹlẹ́rìí Jèhófà bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́ déédéé. Nígbà tó yá, mo gé irún gígùn tó wà lórí mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí í lọ sí gbogbo ìpàdé tí wọ́n ń ṣe ní Gbọ̀ngàn Ìjọba. Àwọn èèyàn máa ń fi ọ̀yàyà kí mi láwọn ìpàdé yẹn, ó sì jẹ́ kó túbọ̀ dá mi lójú pé mo ti wá rí òtítọ́.

 Òtítọ́ kan ni pé tí mo bá fẹ́ fi ohun tí mò ń kọ́ nínú Bíbélì sílò, àfi kí n yí àwọn nǹkan pàtàkì kan pa dà láyé mi. Àkọ́kọ́, mo gbọ́dọ̀ jáwọ́ nínú oògùn olóró tí mò ń lò, kí n sì jáwọ́ nínú ìṣekúṣe. Mo tún gbọ́dọ̀ yí ìwà ìmọtara-ẹni-nìkan tí mo ní pa dà, kí n sì túbọ̀ máa gba tàwọn míì rò. Ohun míì tún ni pé èmi ni mò ń dá tọ́ àwọn ọmọ mi méjèèjì, torí náà, ó yẹ kí n kọ́ bí màá ṣe máa bójú tó wọn, kí n sì máa fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run kọ́ wọn. Bí mo ṣe pa iṣẹ́ orin tí mò ń ṣe tì nìyẹn, tí mo sì wá iṣẹ́ olówó pọ́ọ́kú kan ṣe níléeṣẹ́ kan.

 Kò rọrùn láti ṣe àwọn nǹkan tí mo sọ yìí. Bí mo ṣe ń gbìyànjú láti jáwọ́ lílo oògùn olóró, ara mi kì í lélẹ̀ tí mi ò bá ti lò ó, èyí sì mú kí n tún pa dà sídìí ẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀mélòó kan. (Róòmù 7:​19, 21-​24) Èyí tó le gan-an fún mi láti ṣe ni kí n jáwọ́ nínú ìṣekúṣe. Bákan náà, iṣẹ́ tuntun tí mo ṣẹ̀ṣẹ̀ gbà máa ń tán mi lókun, owó táṣẹ́rẹ́ tí mo sì ń rí níbẹ̀ ò múnú mi dùn. Nígbà tí mo ṣì ń kọrin, wákàtí méjì péré ni màá fi pa owó tí mò ń fi oṣù mẹ́ta ṣiṣẹ́ fún báyìí.

 Àdúrà ràn mí lọ́wọ́ kí n lè fara da àwọn àtúnṣe tó le tí mo ṣe yẹn. Bí mo tún ṣe máa ń ka Bíbélì lójoojúmọ́ ràn mí lọ́wọ́. Àwọn ẹsẹ Bíbélì kan wà tó gbé mi ró gan-an. Ọ̀kan ni 2 Kọ́ríńtì 7:​1, tó rọ àwọn Kristẹni pé kí wọ́n “wẹ ara [wọn] mọ́ kúrò nínú gbogbo ẹ̀gbin ti ẹran ara àti ti ẹ̀mí.” Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ míì tó tún fi mí lọ́kàn balẹ̀ pé ó ṣeé ṣe fún mi láti jáwọ́ nínú àwọn ìwà burúkú tí mò ń hù ni Fílípì 4:​13, tó sọ pé: “Mo ní okun fún ohun gbogbo nípasẹ̀ agbára ìtóye ẹni tí ń fi agbára fún mi.” Jèhófà Ọlọ́run gbọ́ àdúrà mi, ó pa dà jẹ kí òtítọ́ Bíbélì yé mi, ó sì ràn mí lọ́wọ́ kí n lè máa fi ṣèwà hù. Èyí ló sún mi tí mo fi ya ìgbésí ayé mi sí mímọ́ fún un. (1 Pétérù 4:​1, 2) Ọdún 1997 ni mo ṣèrìbọmi, tí mo sì di Ẹlẹ́rìí Jèhófà.

ÀǸFÀÀNÍ TÍ MO TI RÍ

 Ó dá mi lójú pé ká ní ìgbésí ayé tí mò ń gbé tẹ́lẹ̀ náà ni mo ṣì ń gbé, mi ò bá ti kú báyìí. Àmọ́ ayé mi ti nítumọ̀ báyìí, mo sì ń láyọ̀! Ìbùkún ńlá ni Elvie, ìyàwó mi àtàtà jẹ́ fún mi. Òjíṣẹ́ alákòókò kíkún làwa méjèèjì, a jọ ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, a sì ń gbádùn ẹ̀. Èyí ń múnú mi dùn gan-an, ó sì ń fi mí lọ́kàn balẹ̀. Mo dúpẹ́, mo tún ọpẹ́ dá lọ́wọ́ Jèhófà pé ó fà mí sọ́dọ̀ ara rẹ̀.​—Jòhánù 6:​44.