Ìwé Kìíní Jòhánù 3:1-24

  • Ọmọ Ọlọ́run ni wá (1-3)

  • Àwọn ọmọ Ọlọ́run yàtọ̀ sí àwọn ọmọ Èṣù (4-12)

    • Jésù máa fọ́ àwọn iṣẹ́ Èṣù túútúú (8)

  • Ẹ nífẹ̀ẹ́ ara yín (13-18)

  • Ọlọ́run ju ọkàn wa lọ (19-24)

3  Ẹ wo irú ìfẹ́ tí Baba ní sí wa+ tí a fi ń pè wá ní ọmọ Ọlọ́run!+ Ohun tí a sì jẹ́ nìyẹn. Ìdí nìyẹn tí ayé ò fi mọ̀ wá,+ torí kò tíì mọ̀ ọ́n.+  Ẹ̀yin ará mi ọ̀wọ́n, a ti wá di ọmọ Ọlọ́run,+ àmọ́ a ò tíì fi ohun tí a máa jẹ́ hàn kedere.+ A mọ̀ pé nígbà tí a bá fi í hàn kedere a máa dà bíi rẹ̀, torí a máa rí i bó ṣe rí gẹ́lẹ́.  Gbogbo ẹni tó bá sì ní ìrètí yìí nínú rẹ̀ ń wẹ ara rẹ̀ mọ́+ bí ẹni yẹn ṣe jẹ́ mímọ́.  Gbogbo ẹni tó bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà ń rú òfin, ẹ̀ṣẹ̀ ni rírú òfin.  Bákan náà, ẹ mọ̀ pé a fi í hàn kedere láti mú àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa kúrò,+ kò sì sí ẹ̀ṣẹ̀ nínú rẹ̀.  Gbogbo ẹni tó bá wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ̀ kì í sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà;+ ẹnikẹ́ni tó bá sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà kò tíì rí i, kò sì tíì mọ̀ ọ́n.  Ẹ̀yin ọmọ kéékèèké, kí ẹnikẹ́ni má ṣì yín lọ́nà; gbogbo ẹni tó bá ń ṣe òdodo jẹ́ olódodo, bí ẹni yẹn ṣe jẹ́ olódodo.  Ẹni tó bá ń sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà wá látọ̀dọ̀ Èṣù, torí láti ìbẹ̀rẹ̀* ni Èṣù ti ń dẹ́ṣẹ̀.+ Ìdí tí a ṣe fi Ọmọ Ọlọ́run hàn kedere nìyí, kó lè fọ́ àwọn iṣẹ́ Èṣù túútúú.*+  Gbogbo ẹni tí a bí látọ̀dọ̀ Ọlọ́run kì í sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà,+ torí irúgbìn* Rẹ̀ wà nínú ẹni náà, kò sì lè sọ ẹ̀ṣẹ̀ dàṣà, torí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run la ti bí i.+ 10  Ohun tí a máa fi dá àwọn ọmọ Ọlọ́run àti àwọn ọmọ Èṣù mọ̀ nìyí: Ẹnikẹ́ni tí kì í ṣe òdodo kò wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ sì ni ẹni tí kò nífẹ̀ẹ́ arákùnrin rẹ̀.+ 11  Torí ọ̀rọ̀ tí ẹ ti gbọ́ láti ìbẹ̀rẹ̀ ni pé ká nífẹ̀ẹ́ ara wa;+ 12  kì í ṣe bíi Kéènì, tó jẹ́ ti ẹni burúkú náà, tó sì pa àbúrò rẹ̀.+ Kí nìdí tó fi pa á? Torí àwọn iṣẹ́ rẹ̀ burú,+ àmọ́ ti àbúrò rẹ̀ jẹ́ òdodo.+ 13  Ẹ̀yin ará, ẹ má ṣe jẹ́ kó yà yín lẹ́nu pé ayé kórìíra yín.+ 14  A mọ̀ pé a ti tinú ikú wá sí ìyè,+ torí pé a nífẹ̀ẹ́ àwọn ará.+ Ẹni tí kò nífẹ̀ẹ́ ṣì wà nínú ikú.+ 15  Gbogbo ẹni tó bá kórìíra arákùnrin rẹ̀ jẹ́ apààyàn,+ ẹ sì mọ̀ pé kò sí apààyàn kankan tí ìyè àìnípẹ̀kun ṣì wà nínú rẹ̀.+ 16  Ohun tó jẹ́ ká mọ ìfẹ́ ni pé ẹni yẹn fi ẹ̀mí* rẹ̀ lélẹ̀ fún wa,+ torí náà ó di dandan kí àwa náà fi ẹ̀mí wa* lélẹ̀ fún àwọn ará wa.+ 17  Àmọ́ ẹnikẹ́ni tó bá ní ohun ìní ayé yìí, tó sì rí i pé arákùnrin rẹ̀ ṣaláìní síbẹ̀ tí kò ṣàánú rẹ̀, báwo ni ìfẹ́ Ọlọ́run ṣe wà nínú rẹ̀?+ 18  Ẹ̀yin ọmọ kéékèèké, kò yẹ kí ìfẹ́ wa jẹ́ ọ̀rọ̀ ẹnu tàbí ti ahọ́n,+ àmọ́ ó yẹ kó jẹ́ ní ìṣe+ àti òtítọ́.+ 19  Èyí ló máa jẹ́ ká mọ̀ pé a wá látinú òtítọ́, a sì máa jẹ́ kí ọkàn wa balẹ̀* níwájú rẹ̀ 20  nínú ohunkóhun tí ọkàn wa ti lè dá wa lẹ́bi, torí Ọlọ́run ju ọkàn wa lọ, ó sì mọ ohun gbogbo.+ 21  Ẹ̀yin ẹni ọ̀wọ́n, tí ọkàn wa kò bá dá wa lẹ́bi, a lè sọ̀rọ̀ ní fàlàlà níwájú Ọlọ́run;+ 22  a sì ń rí ohunkóhun tí a bá béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ gbà,+ torí à ń pa àwọn àṣẹ rẹ̀ mọ́, a sì ń ṣe àwọn ohun tó dáa lójú rẹ̀. 23  Lóòótọ́, àṣẹ tó pa nìyí pé: ká ní ìgbàgbọ́ nínú orúkọ Ọmọ rẹ̀ Jésù Kristi,+ ká sì nífẹ̀ẹ́ ara wa+ bó ṣe pàṣẹ fún wa gẹ́lẹ́. 24  Bákan náà, ẹni tó bá ń pa àwọn àṣẹ rẹ̀ mọ́ wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú rẹ̀, ó sì máa wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ẹni náà.+ Ẹ̀mí tó fún wa sì jẹ́ ká mọ̀ pé ó wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú wa.+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “kó lè run àwọn iṣẹ́ Èṣù.”
Tàbí “látìgbà tí ó ti bẹ̀rẹ̀.”
Ìyẹn, irúgbìn tó lè méso jáde tàbí kó bí sí i.
Tàbí “ọkàn.”
Tàbí “ọkàn wa.”
Tàbí “máa yí èrò ọkàn wa pa dà; máa mú kó dá ọkàn wa lójú.”