Sí Àwọn Ará Róòmù 10:1-21

  • Bí ọwọ́ èèyàn ṣe lè tẹ òdodo Ọlọ́run (1-15)

    • Ìkéde ní gbangba (10)

    • Kíképe Jèhófà ń yọrí sí ìgbàlà (13)

    • Ẹsẹ̀ àwọn oníwàásù rẹwà (15)

  • Wọ́n kọ ìhìn rere (16-21)

10  Ẹ̀yin ará, ohun rere tó wà lọ́kàn mi àti ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ mi sí Ọlọ́run nítorí wọn ni pé kí wọ́n rí ìgbàlà.+  Nítorí mo jẹ́rìí wọn pé wọ́n ní ìtara fún Ọlọ́run,+ àmọ́ kì í ṣe pẹ̀lú ìmọ̀ tó péye.  Bí wọn ò ṣe mọ òdodo Ọlọ́run,+ àmọ́ tó jẹ́ pé bí wọ́n á ṣe gbé tiwọn kalẹ̀ ni wọ́n ń wá,+ wọn ò fi ara wọn sábẹ́ òdodo Ọlọ́run.+  Nítorí Kristi ni òpin Òfin,+ kí gbogbo ẹni tó ní ìgbàgbọ́ lè ní òdodo.+  Nítorí Mósè kọ̀wé nípa òdodo tó wá látinú Òfin pé: “Yóò mú kí ẹni tó bá ń pa àwọn ohun tó sọ mọ́ wà láàyè.”+  Àmọ́ òdodo tó wá látinú ìgbàgbọ́ sọ pé: “Má sọ lọ́kàn rẹ pé,+ ‘Ta ló máa lọ sí ọ̀run?’+ ìyẹn, láti mú Kristi wá  tàbí, ‘Ta ló máa lọ sínú ọ̀gbun àìnísàlẹ̀?’+ ìyẹn, láti mú Kristi gòkè kúrò nínú ikú.”  Àmọ́ kí ni Ìwé Mímọ́ sọ? “Tòsí rẹ ni ọ̀rọ̀ náà wà, ní ẹnu rẹ àti ọkàn rẹ”;+ ìyẹn, “ọ̀rọ̀” ìgbàgbọ́, tí à ń wàásù.  Nítorí tí o bá ń fi ẹnu rẹ kéde ní gbangba pé Jésù ni Olúwa,+ tí o sì ní ìgbàgbọ́ nínú ọkàn rẹ pé Ọlọ́run gbé e dìde kúrò nínú ikú, a ó gbà ọ́ là. 10  Nítorí ọkàn la fi ń ní ìgbàgbọ́ kí a lè jẹ́ olódodo, àmọ́ ẹnu la fi ń kéde ní gbangba+ kí a lè rí ìgbàlà. 11  Ìwé Mímọ́ sọ pé: “Kò sí ẹni tó bá gbé ìgbàgbọ́ rẹ̀ lé e tó máa rí ìjákulẹ̀.”+ 12  Nítorí kò sí ìyàtọ̀ nínú Júù àti Gíríìkì.+ Torí Olúwa kan náà ló wà lórí gbogbo wọn, ẹni tó lawọ́* sí gbogbo àwọn tó ń ké pè é. 13  Nítorí “gbogbo ẹni tó bá ń ké pe orúkọ Jèhófà* yóò rí ìgbàlà.”+ 14  Àmọ́, báwo ni wọ́n á ṣe ké pè é tí wọn ò bá ní ìgbàgbọ́ nínú rẹ̀? Báwo sì ni wọ́n á ṣe ní ìgbàgbọ́ nínú ẹni tí wọn ò gbọ́ nípa rẹ̀? Báwo ni wọ́n á ṣe gbọ́ tí kò bá sí ẹni tó máa wàásù? 15  Báwo ni wọ́n á sì ṣe wàásù láìjẹ́ pé a rán wọn jáde?+ Gẹ́gẹ́ bó ṣe wà lákọsílẹ̀ pé: “Ẹsẹ̀ àwọn tó ń kéde ìhìn rere àwọn ohun rere mà rẹwà o!”+ 16  Síbẹ̀, kì í ṣe gbogbo wọn ló ṣègbọràn sí ìhìn rere náà. Nítorí Àìsáyà sọ pé: “Jèhófà,* ta ló ti nígbàgbọ́ nínú ohun tó gbọ́ lọ́dọ̀ wa?”*+ 17  Torí náà, ìgbàgbọ́ ń tẹ̀ lé ohun tí a gbọ́.+ Ohun tí a gbọ́ sì jẹ́ nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Kristi. 18  Àmọ́ mo béèrè pé, Ṣé wọn ò gbọ́ ni? Wọ́n kúkú gbọ́. Torí, ní tòótọ́, “ohùn wọn ti dún jáde lọ sí gbogbo ayé, iṣẹ́ tí wọ́n ń jẹ́ sì ti dé ìkángun ilẹ̀ ayé tí à ń gbé.”+ 19  Àmọ́ mo béèrè pé, Ṣé Ísírẹ́lì ò mọ̀ ni?+ Wọ́n kúkú mọ̀. Lákọ̀ọ́kọ́, Mósè sọ pé: “Màá fi àwọn tí kì í ṣe orílẹ̀-èdè mú kí ẹ jowú; màá fi orílẹ̀-èdè òmùgọ̀ mú kí ẹ gbaná jẹ.”+ 20  Àmọ́ Àìsáyà fi ìgboyà sọ̀rọ̀, ó ní: “Àwọn tí kò wá mi ti rí mi,+ àwọn tí kò béèrè mi ti wá mọ̀ mí.”+ 21  Àmọ́, ó sọ nípa Ísírẹ́lì pé: “Láti àárọ̀ ṣúlẹ̀, mo tẹ́ ọwọ́ mi sí àwọn èèyàn tó jẹ́ aláìgbọràn àti olóríkunkun.”+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Ní Grk., “jẹ́ ọlọ́rọ̀.”
Tàbí “ìròyìn wa?”