Lọ wo ohun tó wà nínú rẹ̀

Lọ wo àwọn ohun tó wà

ORIN 27

Ọlọ́run Máa Ṣí Àwọn Ọmọ Rẹ̀ Payá

Ọlọ́run Máa Ṣí Àwọn Ọmọ Rẹ̀ Payá

(Róòmù 8:19)

  1. 1. Jáà ti yan àwọn ọmọ rẹ̀.

    Ó máa ṣí wọn payá.

    Wọ́n máa jọba pẹ̀lú Kristi.

    Ẹ̀dá ẹ̀mí ni wọ́n.

    (ÈGBÈ)

    Jáà ṣí àwọn ‘mọ rẹ̀ payá

    Pẹ̀lú Jésù Kristi.

    Wọ́n máa jagun, wọ́n máa ṣẹ́gun.

    Jáà yóò san wọ́n lẹ́san.

  2. 2. Láìpẹ́, àwọn tó bá ṣẹ́ kù

    Máa gbọ́ ìpè ‘kẹyìn.

    Olúwa àwọn olúwa

    Yóò gbà wọ́n sọ́dọ̀ rẹ̀.

    (ÈGBÈ)

    Jáà ṣí àwọn ‘mọ rẹ̀ payá

    Pẹ̀lú Jésù Kristi.

    Wọ́n máa jagun, wọ́n máa ṣẹ́gun.

    Jáà yóò san wọ́n lẹ́san.

    (ÀSOPỌ̀)

    Kristi àtàwọn ọmọ Jáà

    Máa jagun ìkẹyìn.

    ’Gbéyàwó Ọ̀dọ́ Àgùntàn

    Máa wà títí ayé.

    (ÈGBÈ)

    Jáà ṣí àwọn ‘mọ rẹ̀ payá

    Pẹ̀lú Jésù Kristi.

    Wọ́n máa jagun, wọ́n máa ṣẹ́gun.

    Jáà yóò san wọ́n lẹ́san.