Sáàmù 91:1-16

  • Ààbò ní ibi ìkọ̀kọ̀ Ọlọ́run

    • Ó gbà á lọ́wọ́ pẹyẹpẹyẹ (3)

    • Ààbò lábẹ́ ìyẹ́ apá Ọlọ́run (4)

    • Bí ẹgbẹẹgbẹ̀rún tilẹ̀ ṣubú, nǹkan kan ò ní ṣe ọ́ (7)

    • Ọlọ́run pàṣẹ fún àwọn áńgẹ́lì láti máa ṣọ́ ọ (11)

91  Ẹni tó bá ń gbé ibi ìkọ̀kọ̀ Ẹni Gíga Jù Lọ+Yóò máa gbé lábẹ́ òjìji Olódùmarè.+   Màá sọ fún Jèhófà pé: “Ìwọ ni ibi ààbò mi àti odi ààbò mi,+Ọlọ́run mi tí mo gbẹ́kẹ̀ lé.”+   Nítorí yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ pańpẹ́ pẹyẹpẹyẹ,Lọ́wọ́ àjàkálẹ̀ àrùn tó ń pani run.   Yóò fi àwọn ìyẹ́ tó fi ń fò bò ọ́,*Wàá sì fi abẹ́ ìyẹ́ apá rẹ̀ ṣe ibi ààbò.+ Òtítọ́ rẹ̀+ yóò jẹ́ apata+ ńlá àti odi* ààbò.   O ò ní bẹ̀rù àwọn ohun tó ń kó jìnnìjìnnì báni ní òru+Tàbí ọfà tó ń fò ní ọ̀sán+   Tàbí àjàkálẹ̀ àrùn tó ń yọ́ kẹ́lẹ́ nínú òkùnkùnTàbí ìparun tó ń ṣọṣẹ́ ní ọ̀sán gangan.   Ẹgbẹ̀rún yóò ṣubú ní ẹ̀gbẹ́ rẹÀti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Àmọ́ kò ní sún mọ́ ọ.+   Ojú rẹ nìkan ni wàá fi rí iBí o ṣe ń wo ìyà* àwọn ẹni burúkú.   Nítorí o sọ pé: “Jèhófà ni ibi ààbò mi,”O ti fi Ẹni Gíga Jù Lọ ṣe ibùgbé* rẹ;+ 10  Àjálù kankan kò ní bá ọ,+Àjàkálẹ̀ àrùn kankan kò sì ní sún mọ́ àgọ́ rẹ. 11  Torí ó máa pàṣẹ fún àwọn áńgẹ́lì rẹ̀ nítorí rẹ,+Láti máa ṣọ́ ọ ní gbogbo ọ̀nà rẹ.+ 12  Wọ́n á fi ọwọ́ wọn gbé ọ,+Kí o má bàa fi ẹsẹ̀ rẹ gbá òkúta.+ 13  Wàá rìn kọjá lórí ọmọ kìnnìún àti ṣèbé;Wàá tẹ kìnnìún onígọ̀gọ̀* àti ejò ńlá mọ́lẹ̀.+ 14  Ọlọ́run sọ pé: “Nítorí ó nífẹ̀ẹ́ mi,* màá gbà á sílẹ̀.+ Màá dáàbò bò ó torí pé ó mọ* orúkọ mi.+ 15  Yóò ké pè mí, màá sì dá a lóhùn.+ Màá dúró tì í nígbà wàhálà.+ Màá gbà á sílẹ̀, màá sì ṣe é lógo. 16  Màá fi ẹ̀mí gígùn tẹ́ ẹ lọ́rùn,+Màá sì jẹ́ kó rí àwọn iṣẹ́ ìgbàlà mi.”*+

Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé

Tàbí “bo ọ̀nà àbáwọlé rẹ.”
Tàbí “ògiri.”
Ní Héb., “ẹ̀san.”
Tàbí kó jẹ́, “ibi ààbò; odi ààbò.”
Tàbí “kìnnìún tó tó ọdẹ ṣe.”
Ní Héb., “ó ti dara pọ̀ mọ́ mi.”
Tàbí “bọlá fún.”
Tàbí “rí ìgbàlà láti ọ̀dọ̀ mi.”